Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?
Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?
Kí Ni Kò Tọ̀nà Nínú Àwòrán Yìí?
Ka Ìṣe 8:26-40. Wo àwòrán yìí. Àwọn nǹkan wo ni kò tọ̀nà nínú àwòrán náà? Kọ ìdáhùn rẹ sórí àwọn ìlà yìí.
1. ․․․․․
2. ․․․․․
3. ․․․․․
FÚN ÌJÍRÒRÒ:
Kí nìdí tí ìwẹ̀fà yẹn kò fi lóye ohun tó ń kà? Ta ló ràn án lọ́wọ́ tó fi lóye ohun tó ń kà? Àwọn ọ̀nà wo lo lè gbà fara wé ìwẹ̀fà yẹn?
Nínú Ìtẹ̀jáde Yìí
Dáhùn àwọn ìbéèrè yìí, kó o sì kọ (àwọn) ẹsẹ Bíbélì tó yẹ sínú àlàfo.
OJÚ ÌWÉ 3 Ẹni tí kò bá pèsè fún ìdílé rẹ̀ burú ju ta ni lọ? 1 Tímótì 5:․․․
OJÚ ÌWÉ 16 Bó bá dọ̀rọ̀ ìrísí wa, kí ló yẹ ká fi sọ́kàn? 1 Pétérù 3:․․․
OJÚ ÌWÉ 24 Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ kí ló yẹ kó o ṣe? Róòmù 12:․․․
OJÚ ÌWÉ 27 Ká bàa lè máa láyọ̀, kí ló gbọ́dọ̀ máa jẹ wá lọ́kàn? Mátíù 5:․․․
Kí Lo Mọ̀ Nípa Jẹ́fútà Onídàájọ́?
Ka Àwọn Onídàájọ́ 11:1–12:7. Dáhùn àwọn ìbéèrè wọ̀nyí.
4. ․․․․․
Èwo lára ẹ̀yà Ísírẹ́lì méjìlá ló ti wá?
AMỌ̀NÀ: Wo Númérì 26:29.
5. ․․․․․
Ọwọ́ orílẹ̀-èdè wo ló ti gba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀?
6. ․․․․․
Bẹ́ẹ̀ ni tàbí rárá? Ó gbé ayé lẹ́yìn Jósẹ́fù, ọmọkùnrin Jákọ́bù (Ísírẹ́lì).
FÚN ÌJÍRÒRÒ:
Kí lo rò pé ó mú kí ọmọbìnrin Jẹ́fútà fọwọ́ sowọ́ pọ̀ kí bàbá rẹ̀ lè mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ṣẹ? Báwo lo ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ọmọbìnrin Jẹ́fútà?
ÌDÁHÙN SÍ ÌBÉÈRÈ
1. Ó jọ pé Fílípì nìkan ló dá wà.
2. Kẹ̀kẹ́ ẹṣin ni ìwẹ̀fà yẹn gùn kì í ṣe ẹṣin.
3. Aṣálẹ̀ ni ìṣẹ̀lẹ̀ yẹn ti wáyé kì í ṣe àárín ìlú téèyàn pọ̀ sí.
4. Mánásè.—Númérì 26:29; Àwọn Onídàájọ́ 11:1.
5. Ámónì—Àwọn Onídàájọ́ 11:4.
6. Òótọ́.