Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

March 22, 2008—Ọjọ́ Kan Tó Yẹ Ká Rántí

March 22, 2008—Ọjọ́ Kan Tó Yẹ Ká Rántí

March 22, 2008—Ọjọ́ Kan Tó Yẹ Ká Rántí

Lálẹ́ ọjọ́ tó ṣáájú ọjọ́ tí Jésù kú, ó fún àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ ní ìṣù búrẹ́dì kan àti ife wáìnì kan, ó ní kí wọ́n jẹ búrẹ́dì náà, kí wọ́n sì mu wáìnì náà. Ó tún sọ fún wọn pé: “Ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.”—Lúùkù 22:19.

Lọ́dún yìí, ọjọ́ Sátidé, March 22, lẹ́yìn tí oòrùn bá ti wọ̀ ni ọjọ́ tí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí bọ́ sí. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa pàdé pọ̀ níbi gbogbo káàkiri ayé lálẹ́ ọjọ́ pàtàkì yìí láti ṣe Ìrántí Ikú Kristi, lọ́nà tí Jésù ní ká gbà ṣe é. Tìfẹ́tìfẹ́ la fi pè ọ́ sí ìpàdé yìí kó o wá bá wa ṣe é. Jọ̀wọ́ kàn sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ kí wọ́n lè sọ àkókò àti ibi tí wọ́n á ti ṣe ìpàdé náà fún ọ.